Published On Dec 13, 2021
Kò ṣeé ṣe láti sọ ìtàn Àláàfin Aólẹ̀ àti Ààrẹ Ọ̀nà Kakaǹfò Àfọ̀njá láì mẹ́nuba ìtàn ìlú Ìwéré ilé. Àwọn ohun tó yẹ kí ẹ mọ̀ nípa ìlú yìí bí: (Ohun tí ó bí orúkọ ìlú yìí, àwọn èèwọ wọn, ìdí tí ogun kìí fi í jà wọ́n, Ìgbéṣẹ̀ tí wọ́n gbé tí ogun Ìdàhòmì ò fi run wọ́n abbl.) ni a mẹ́nuba nínú ìfọ̀rọ̀wánilẹ́nuwò wa pẹ̀lú Kábíyèsí Ọba Rev. Evang. John O. Ola Ọdẹ́dòkun Ayinla III, Oníwèéré ti Ìwéré ilé ní Ọjọ́rú, ọjọ́ kẹjọ oṣù Kejìlá ọdún 2021.
show more